Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 24:8-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Ẹlẹ́kẹta sì ni Hárímù,ẹ̀kẹ́rin sì ní Ṣéórímù,

9. Ẹ̀karùn-ún sì ni Maíkíyà,ẹlẹkẹ́fà sì ni Míjámínì,

10. Ẹ̀kẹ́je sì ni Hakósì,ẹlẹ́kẹ́jọ sí ni Ábíjà,

11. Ẹkẹ́sàn sì ni Jésúà,ẹ̀kẹ́wà sì ni Ṣékáníà,

12. Ẹ̀kọ́kànlá sì ni Élíásíbù,ẹlẹ́kẹjìlá sì ni Jákímù,

13. Ẹ̀kẹtàlá sì ni Húpà,ẹlẹ́kẹrìnlá sì ni Jéṣébéábù,

14. Ẹkẹdógun sì ni Bílígà,ẹ̀kẹ́rìndílogún sì ni Ímerì

15. Ẹ̀kẹtàdílógún sì ni Héṣírì,ekejìdílógún sì ni Háfísesì,

16. Ẹ̀kọkàndílógún sì ni Pétalà,ogún sì ni Jéhésékélì,

17. Ẹ̀kọ́kànlélógún sì ni Jákínì,ẹ̀kẹ́rìnlélogún sì ni Gámúlì,

18. Ẹ̀kẹtàlélógún sì ni Déláyà,ẹ̀kẹrìnlélógún sì ni Másíà.

19. Àwọn wọ̀nyí ni a yàn fún iṣẹ́ ìsìn nígbà tí wọ́n wọ ilé Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìlànà àti àṣẹ tí a ti fi fún wọn láti ọwọ́ baba ńlá wọn Árónì gẹ́gẹ́ bí Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, tí pàṣẹ fun wọn.

20. Ìyòókù àwọn ọmọ Léfì:láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ámúríamù: Ṣúbáelì;láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ṣúbáélì; Jédeíà.

21. Àti gẹ́gẹ́ bí Réhábíà, láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Réhábíà:Íṣíà sì ni alákọ́kọ́.

22. Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Iṣárì: Ṣélómótì;láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ṣélomótì: Jáhátì.

23. Àwọn ọmọ Hebúrónì: Jéríyà alákọ́kọ́, Ámáríyà elẹ́kẹjì, Jáhásélì ẹlẹ́kẹta àti Jékáméámù ẹlẹ́kẹrin.

24. Àwọn ọmọ Húsíélì: Mikà;nínú àwọn ọmọ Míkà: Ṣámírù.

25. Àwọn arákùnrin Míkà: Íṣíà;nínú àwọn ọmọ Íṣíà: Ṣekaríyà.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 24