Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 24:18-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Ẹ̀kẹtàlélógún sì ni Déláyà,ẹ̀kẹrìnlélógún sì ni Másíà.

19. Àwọn wọ̀nyí ni a yàn fún iṣẹ́ ìsìn nígbà tí wọ́n wọ ilé Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìlànà àti àṣẹ tí a ti fi fún wọn láti ọwọ́ baba ńlá wọn Árónì gẹ́gẹ́ bí Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, tí pàṣẹ fun wọn.

20. Ìyòókù àwọn ọmọ Léfì:láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ámúríamù: Ṣúbáelì;láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ṣúbáélì; Jédeíà.

21. Àti gẹ́gẹ́ bí Réhábíà, láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Réhábíà:Íṣíà sì ni alákọ́kọ́.

22. Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Iṣárì: Ṣélómótì;láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ṣélomótì: Jáhátì.

23. Àwọn ọmọ Hebúrónì: Jéríyà alákọ́kọ́, Ámáríyà elẹ́kẹjì, Jáhásélì ẹlẹ́kẹta àti Jékáméámù ẹlẹ́kẹrin.

24. Àwọn ọmọ Húsíélì: Mikà;nínú àwọn ọmọ Míkà: Ṣámírù.

25. Àwọn arákùnrin Míkà: Íṣíà;nínú àwọn ọmọ Íṣíà: Ṣekaríyà.

26. Àwọn ọmọ Mérarì: Málì àti Múṣì.Àwọn ọmọ Jásíà: Bẹ́nò.

27. Àwọn ọmọ Mérárì:Lati Jasíà: Bẹ́nò, Ṣóhámù, Ṣákúrì àti Íbírì.

28. Láti Málì: Élíásérì, ẹni tí kò ni àwọn ọmọ.

29. Láti Kíṣì: Àwọn ọmọ Kíṣì:Jérámélì.

30. Àti àwọn ọmọ Muṣì: Málì, Édérì àti Jérímotì.Èyí ni àwọn ọmọ Léfì, gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.

31. Wọ́n sì ṣé kèké gẹ́gẹ́ bí àwọn arákùnrin wọn àwọn ọmọ Árónì ṣe ṣẹ́, níwáju ọba Dáfídì àti Ṣádókì, Áhímélékì, àti olórí ìdílé àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Léfì. Àwọn ìdilé àgbààgbà arákùnrin wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀ lórí àwọn arakùnrin wọn kéékèèkéé.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 24