Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 21:8-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Nígbà náà Dáfídì sọ fún Ọlọ́run pé, Èmi ti dẹ́ṣẹ̀ gidìgidì nípa ṣíṣe èyí. Nísinsin yìí, èmi bẹ̀ ọ́, mú ìjẹ̀bi àwọn ìránṣẹ́ rẹ kúrò. Èmi ti hùwà òmùgọ̀ gidigidi.

9. Olúwa sì fi fún Gádì, aríran Dáfídì pé.

10. “Lọ kí o lọ sọ fún Dáfídì pé, ‘Èyí ní ohun tí Olúwa sọ: Èmi sì fún ọ ní àwọn àṣàyàn mẹ́ta. Yan ọ̀kan ninú wọn fún mi láti gbé jáde nípa rẹ.’ ”

11. Bẹ́ẹ̀ ni Gádì lọ sí ọ̀dọ̀ Dáfídì ó sì wí fún pé, “Nǹkan yí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Yan aṣàyàn tìrẹ:

12. Ọdún mẹ́ta ìyàn, oṣù mẹ́ta gbígbá lọ niwájú àwọn ọ̀tá rẹ, pẹ̀lú idà wọn láti lé ọ bá, tàbí ọjọ́ mẹ́fà idà Olúwa ọjọ́ àjàkálẹ̀-àrùn ní ilẹ̀ náà, pẹ̀lú àwọn ángẹ́lì Olúwa láti pa gbogbo agbègbè Ísírẹ́lì run.’ Nísinsi yìí ǹjẹ́, ronú bí èmi yóò ti ṣe dá ẹni tí ó rán mi lóhùn.”

13. Dáfídì sì wí fún Gádì pé èmi wà nínú ìyọnu ńlá. Jẹ́ kí èmi kí ó ṣubú sí ọwọ́ Olúwa, nítorí tí àánú Rẹ̀ pọ̀ gidigidi; Ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí èmi kí o ṣubú sí ọwọ́ àwọn ènìyàn.

14. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa rán àjàkálẹ̀-àrùn lórí Ísírẹ́lì, ẹgbàá márùndínlógójì (70,000) ènìyàn Ísírẹ́lì sì kú.

15. Ọlọ́run sì rán ańgẹ́lì láti pa Jérúsálẹ́mù run. Ṣùgbọ́n bí áńgẹ́lì ti ń ṣe èyí, Olúwa sì ríi. Ó sì káàánú nítorí ibi báà, ó sì wí fún áńgẹ́lì tí ó pa àwọn ènìyàn náà run pé, “Ó ti tó! Dá ọwọ́ rẹ dúró.” Ańgẹ́lì Olúwa náà sì dúró níbi ilẹ̀ ìpakà Áráúnà ará Jébúsì.

16. Dáfídì sì wòkè ó sì rí áńgẹ́lì Olúwa dúró láàrin ọ̀run àti ayé pẹ̀lú idà fífàyọ ní ọwọ́ Rẹ̀ tí ó sì nàá sórí Jérúsálẹ́mù. Nígbà náà Dáfídì àti àwọn àgbààgbà, sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da ojú wọn bolẹ̀.

17. Dáfídì sì wí fún Ọlọ́run pé, “Èmi ha kọ́ ni mo paláṣẹ àti ka àwọn jagunjagun ènìyàn? Èmi ni ẹni náà tí ó dẹ́ṣẹ̀ tí ó sì ṣe ohun tí kò dára, wọ̀nyí ni àgùntàn. Kí ni wọ́n ṣe? Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà lára mi àti àwọn ìdíle mi, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí àjàkálẹ̀-àrùn yìí kí ó dúró lóri àwọn ènìyàn rẹ.”

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 21