Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 2:40-55 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

40. Éléáṣáì ni baba Ṣísámálì,Ṣísámálì ni baba Ṣálúmù,

41. Ṣálúmù sì ni baba Élísámà.

42. Àwọn ọmọ Kálébù arákùnrin Jérámélì:Méṣà àkọ́bí Rẹ̀, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Ṣífì àti àwọn ọmọ Rẹ̀ Méréṣà, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Hébúrónì.

43. Àwọn ọmọ Hébúrónì:Kórà, Tápúà, Rékémù, àti Ṣémà.

44. Ṣémà ni baba Ráhámú Ráhámù sì jẹ́ baba fún Jóríkéámù. Rékémù sì ni baba Ṣémáì.

45. Àwọn ọmọ Ṣémáì ni Máónì, Máónì sì ni baba Bétí-Ṣúri.

46. Éfà Obìnrin Kélẹ́bù sì ni ìyá Hárà nì, Mósà àti Gásésì, Háránì sì ni baba Gásésì.

47. Àwọn ọmọ Jádáì:Régémù, Jótamù, Gésánì, Pétélì, Éfà àti Ṣáfù.

48. Mákà obìnrin Kélẹ́bù sì ni ìyá Ṣébérì àti Tíránà.

49. Ó sì bí Ṣáfà baba Mákíbénà, Ṣéfà baba Mákíbénà àti baba Gíbéà: ọmọbìnrin Kélẹ́bù sì ni Ákíṣà.

50. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Kélẹ́bù.Àwọn ọmọ Húrì, àkọ́bí Éfúrátà:Ṣóbálì baba Kiriati-Jéárímù.

51. Ṣálímà baba Bétíléhẹ́mù àti Háréfù baba Bẹti-Gádérì.

52. Àwọn ọmọ Ṣóbálì baba Kíríátì-Jéárímù ni:Háróè, ìdajì àwọn ará Mánáhítì.

53. Àti ìdílé Kíríátì-Jéárímù: àti àwọn ara Ítírì, àti àwọn ará Pútì, àti àwọn ará Ṣúmátì àti àwọn ará Mísíhí-ráì: láti ọ̀dọ̀ wọn ni àwọn ọmọ ará Sórátì àti àwọn ará Ésítaólì ti wá.

54. Àwọn ọmọ Ṣálímà:Bẹ́tílẹ́hẹ́mù, àti àwọn ará Nétófátì, Atírótì Bẹti-Jóábù, ìdajì àwọn ará Mánátì, àti Ṣórì,

55. Àti àwọn ìdílé àwọn akọ̀wé, ẹni tí ń gbé ní Jábésì: àti àwọn ọmọ Tírátì àti àwọn ará Ṣíméátì àti àwọn ará Ṣúkátì. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ará Kénì, ẹni tí ó wá láti ọ̀dọ̀ Hámátì, baba ilé Kélẹ́bù.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 2