Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 2:14-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Ẹlẹ́ẹ̀kẹrin Nàtaníẹ́lì, ẹlẹ́ẹ̀káàrùn-ún Rádáì,

15. ẹlẹ́ẹ̀kẹfà Ósémù àti ẹlẹ́ẹ̀keje Dáfídì.

16. Àwọn arábìnrin wọn ni Ṣérúà àti Ábígáílì. Àwọn ọmọ mẹ́ta Ṣérúà ni Ábíṣáì, Jóábù àti Ásáélì.

17. Ábígáílì ni ìyá Ámásà, ẹni tí baba Rẹ̀ sì jẹ́ Jétérì ará Íṣímáẹ́lì.

18. Kélẹ́bù ọmọ Hésírónì ní ọmọ láti ọ̀dọ̀ ìyàwó Rẹ̀ Ásúbà (láti ọ̀dọ̀ Jéríótù). Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Rẹ̀: Jéṣérì, Ṣóbábù àti Árídónì.

19. Nígbà tí Ásúbà sì kú, Kélẹ́bù sì fẹ́ Éfúrátì ní aya, ẹni tí ó bí Húrì fún un.

20. Húrì ni baba Úrù, Úrù sì jẹ́ baba Bésálélì.

21. Nígbà tí ó yá, Hésírónì sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ọmọbìnrin Mákírì baba Gílíádì (ó sì ti fẹ́ ní aya láti ìgbà tí ó ti wà ní ẹni ọgọ́ta ọdún) ó sì bí Ṣégúbù.

22. Ṣégúbù sì jẹ́ bàbá Jáírì, ẹni tí ó jẹ́ olùdarí ìlú mẹ́talélógún ní ilẹ̀ Gílíádì.

23. (Ṣùgbọ́n Gésúrì àti Árámù sì fi agbára gba Hafoti Jáírì, àti Kénátì pẹ̀lú gbogbo agbégbé Rẹ̀ tí wọn tẹ̀dó sí jẹ́ ọgọ́ta ìlú.) Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Mákírì Baba Gílíádì.

24. Lẹ́yìn tí Hésírónì sì kú ni Kélẹ́bù Éfúrátà, Ábíà ìyàwó Rẹ̀ ti Hésírónì sì bí Áṣúrì baba Tẹ́kóà fún un

25. Ọmọ Jéráhímélì àkọ́bí Hésírónì:Rámà ọmọ àkọ́bí Rẹ̀ Búnà, Órénì, óṣémù àti Áhíjà.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 2