Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 16:4-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ó yan díẹ̀ lára àwọn ará Léfì láti máa jọ́sìn níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti láti ṣe ìrántí àti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa, Ọlọ́run Ísírélì.

5. Ásáfù jẹ́ olóyè Ṣémírámótì, Jéhíelì, Mátítíyà, Élíábìlì, Bénáyà, Obedi-Édómù àti Jélíélì, Àwọn ni yóò lu lẹ́rì àti dùùrù háàpù. Ásáfù ni yóò lu símíbálì kíkan.

6. Àti Bénáià àti Jahaṣíélì àwọn àlùfáà ni yóò fọn ipè dédé níwájú àpótí ẹ̀rí méjẹ̀mú ti Ọlọ́run.

7. Ní ọjọ́ náà Dáfídì kọ́kọ́ fi lé Ásáfù àti àwon ẹlẹgbẹ́ Rẹ̀ lọ́wọ́ orin Dáfídì ti ọpẹ́ sí Olúwa:

8. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ẹ pe orúkọ Rẹ̀,ẹ fi iṣẹ́ Rẹ̀ hàn nínú àwọn ènìyàn fún ohun tí ó ṣe

9. Ẹ kọrin síi, ẹ kọrin ìyìn, síi,Ẹ sọ ti gbogbo iṣẹ́ ìyanu Rẹ̀

10. Ìyìn nínú orúkọ Rẹ̀ mímọ́;jẹ kí ọkàn àwọn tí ó yin Olúwa kí ó yọ̀.

11. Ẹ wá Olúwa àti agbára Rẹ̀;O wá ojú Rẹ̀ nígbà gbogbo.

12. Rántí àwọn ìyanu tí Ó ti ṣe,isẹ́ ìyanu Rẹ̀ àti ídájọ́ tí Ó ti sọ.

13. A! èyin ìran ọmọ Ísírẹ́lì ìránṣẹ́ Rẹ̀,àwon ọmọ Jákọ́bù, ẹ̀yin tí ó ti yàn.

14. Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa;ìdájọ́ Rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.

15. Ó ránti májẹ̀mú rẹ́ títí láé,ọ̀rọ̀ tí Ó pa láṣẹ fún ẹgbẹ̀rún ìran,

16. Májẹ̀mu tí ó dá pẹ̀lú Ábúráhámù,ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Ísákì.

17. Ó ṣe ìdánilójú u Rẹ̀ fún Jákọ́bù gẹ́gẹ́ bí òfin,sí Ísírẹ́lì gẹ́gẹ́ bí májẹ̀mú láéláé.

18. “Sí ọ, ni Èmi yóò fún ní ilẹ̀ Kénánì.Gẹ́gẹ́ bí àyè tí ìwọ yóò jogún.”

19. Nígbà tí wọn kéré ní iye,wọ́n kéré gidigidi, wọ́n sì jẹ́ àlejò níbẹ̀,

20. wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀ èdè sí orílẹ̀-èdèláti ìjọba kan sí èkejì.

21. Kò gba ọkùnrin kankan láyè láti pọ́n wọn lójú;nítorí ti wọn, ó bá àwọn ọba wí.

22. “Má ṣe fọwọ́ kan àwọn ẹni àmì òróró mi;Má ṣe pa àwọn wòlíì mi lára.”

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 16