Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 12:6-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Élíkánà, Íṣái, Ásárélì, Jóésérì àti Jáṣóbéà ará kórà;

7. Àti Jóélà, àti Ṣébádíà àwọn ọmọ Jéróhámù láti Gédárì.

8. Díẹ̀ lára àwọn ará Gádì yà sọ́dọ̀ Dáfídì ní ibi gíga ní ihà. Wọ́n sì jẹ́ onígboyà ológun tí ó múra fún ogun tí ó sì lágbára láti di àṣà àti ẹsin mú. Ojú wọn sì dàbí ojú kìnìún, wọ́n sì yára bí àgbọ̀nrín lórí àwọn òkè.

9. Ésérì sì jẹ́ ìjòyè,Ọbádáyà sì jẹ́ igbékejì akọgun, Élíábù ẹlẹ́kẹ́ta,

10. Míṣimánà ẹlẹ́kẹ́rin, Jeremíà ẹlẹ́ẹ̀kárùn-ún

11. Átaì ẹlẹ́kẹ́fà, Ẹlíélì èkéje,

12. Jóhánánì ẹlẹ́kẹ́jọ Élísábádì ẹlẹ́ẹ̀kẹ́sàn-án

13. Jeremíàh ẹlẹ́kẹ́wàá àti Mákíbánáì ẹlẹ́kọ́kànlá.

14. Àwọn ará Gádì wọ́n sì jẹ́ olórí ogun; ẹni tí ó kéré jù sì jẹ́ àpapọ̀ ọgọ́rùn-ún, àti fún ẹni tí ó pọ̀jù fún ẹgbẹ̀rún.

15. Àwọn ni ẹni tí ó rékọjá Jọ́dánì ní oṣù àkọ́kọ́ nígbà tí ó kún bo gbogbo bèbè Rẹ̀, wọ́n sì lé gbogbo àwọn tí ó ń gbé nínú àfonífojì, lọ sí ìlà oòrùn àti níhà ìwọ̀ oòrùn.

16. Ìyòókù ará Bẹ́ńjámínì àti àwọn díẹ̀ ọkùnrin láti Júdà lọ sí ọ̀dọ̀ Dáfídì ní ibi gíga.

17. Dáfídì sì lọ láti lọ pàdé wọn ó sì wí fún wọn pé, “Tí ẹ bá wá sọ́dọ̀ mi lálàáfíà, láti ràn mí lọ́wọ́ mo sẹtan láti mú un yín wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú mi ṣùgbọ́n tí ẹ bá wá láti dá mi sí fún àwọn ọ̀ta mi nígbà tí ọwọ́ mi bá mọ́ kúrò nínú ìwà agbára, kí Ọlọ́run àwọn baba wa kí ó sì ri kí ó sì ṣe ìdájọ́.”

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 12