48. Ó rí i pé pẹlu ipá ni wọ́n fi ń wa ọkọ̀, nítorí afẹ́fẹ́ ṣọwọ́ òdì sí wọn. Ó tó bí agogo mẹta òru kí Jesu tó máa lọ sọ́dọ̀ wọn. Ó ń rìn lórí omi, ó fẹ́ kọjá lára wọn.
49. Nígbà tí wọn rí i tí ó ń rìn lórí omi, wọ́n ṣebí iwin ni, wọ́n bá kígbe.
50. Nítorí gbogbo wọn ni wọ́n rí i tí ẹ̀rù sì bà wọ́n.Ṣugbọn lójú kan náà ó fọhùn sí wọn, ó ní, “Ẹ fi ọkàn balẹ̀. Èmi ni. Ẹ má bẹ̀rù.”
51. Ó bá wọ inú ọkọ̀ tọ̀ wọ́n lọ, afẹ́fẹ́ bá rọlẹ̀. Ẹnu yà wọ́n lọpọlọpọ,
52. nítorí pé iṣẹ́ ìyanu ti burẹdi kò yé wọn, nítorí òpè ni wọ́n.