18. kò ní jẹ́ kí n mí,ìbànújẹ́ ni ó fi kún ọkàn mi.
19. Bí ó bá ṣe ti pé kí á dán agbára wò ni,agbára rẹ̀ pọ̀ tayọ!Bí ó bá sì jẹ́ pé ti ọ̀rọ̀ ẹ̀tọ́,ta ló lè pè é lẹ́jọ́?
20. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n kò lẹ́bi,sibẹsibẹ ọ̀rọ̀ ẹnu mi yóo di ẹ̀bi rù mí;bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé n kò lẹ́ṣẹ̀,sibẹsibẹ yóo fihàn pé ẹlẹ́ṣẹ̀ ni mí.
21. N kò lẹ́bi,sibẹ n kò ka ara mi kún,ayé sú mi.
22. Kò sí ìyàtọ̀ lójú rẹ̀,nítorí náà ni mo fi wí pé,ati ẹlẹ́bi ati aláìlẹ́bi ni ó ti parun.
23. Nígbà tí nǹkan burúkú bá ṣẹlẹ̀,tí ó já sí ikú òjijì,a máa fi aláìṣẹ̀ ṣe ẹlẹ́yà ninu ìdààmú wọn.
24. A ti fi ayé lé àwọn ẹni ibi lọ́wọ́,ó ti di àwọn adájọ́ rẹ̀ lójú.Bí kì í bá ṣe òun Ọlọrun,ta ló tún tó bẹ́ẹ̀?
25. “Ọjọ́ ayé mi ń sáré lọ tete,kò sí ẹyọ ọjọ́ kan tí ó dára ninu wọn.
26. Wọ́n sáré kọjá lọ bíi koríko ojú omi,bí ẹyẹ idì tí ń fò fẹ̀ẹ̀ lọ bá ohun tí ó fẹ́ pa.
27. Bí mo bá sọ pé kí n gbàgbé ìráhùn mi,kí n sì tújúká;kí n má ronú mọ́;
28. ẹ̀rù ìrora mi á bẹ̀rẹ̀ sí bà mí,nítorí mo mọ̀ pé o kò ní gbà pé n kò dẹ́ṣẹ̀.
29. Níwọ̀n ìgbà tí a ti dá mi lẹ́bi,kí ni mo tún ń ṣe wahala lásán fún?
30. Ọṣẹ yòówù tí mo lè fi wẹ̀,kódà kí n fi omi yìnyín fọ ọwọ́,
31. sibẹ o óo tì mí sinu kòtò ìdọ̀tí.Kódà n óo di ohun ìríra sí aṣọ ara mi.