1. Wọ̀nyí ni àwọn òwé mìíràn tí Sólómónì pa, tí àwọn ọkùnrin Hẹsikáyà ọba Júdà dà kọ.
2. Ògo Olúwa ní láti fi ọ̀rọ̀ kan pamọ́;láti rí ìdí ọ̀rọ̀ kan ni ògo àwọn ọba.
3. Bí ọ̀run ṣe ga tó tí ayé sì jìnbẹ́ẹ̀ ni ó ṣòro láti mọ èrò ọkàn ọba.
4. Mú ìdàrọ́ kúrò lára fàdákàohun èlò yóò sì jáde fún alágbẹ̀dẹ fàdákà
5. mú ènìyàn búburú kúrò níwájú ọbaa ó sì fìdí ìtẹ́ rẹ múlẹ̀ nípaṣẹ̀ òdodo.
6. Má ṣe gbé ara rẹ ga níwájú ọba,má sì ṣe jìjàdù ààyè láàrin àwọn ènìyàn pàtàkì
7. Ó sàn kí ó wí fún ọ pé, “Gòkè wá síhìn ín”ju wí pé kí ó dójú tì ọ́ níwájú ènìyàn pàtàkì.
8. Ohun tí o ti fi ojú ara rẹ rímá ṣe kánjú gbé e lọ sílé ẹjọ́ nítorí kí ni ìwọ yóò ṣe ní ìgbẹ̀yìnbí aládùúgbò rẹ bá dójú tì ọ́?