17. Góòlù àti òkúta Kírísítalì kò tóẹgbẹ́rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èló wúrà ṣe pàsípààrọ̀ rẹ̀.
18. A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta Jásípérì;iye ọgbọ́n sì ju òkúta Rubì lọ.
19. Òkùta tópásì ti Kúsì kò tóẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.
20. “Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá?Tàbí níbo ni òye ń gbé?
21. A rí i pé, ó farasinko kúrò ní ojúàwọn alààyè gbogbo, ó sì fara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
22. Ibi ìparun (Ábádónì) àti ikú wípé, àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
23. Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nàrẹ̀, òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé
24. Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé, ósì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
25. Láti dà òṣùwọ̀n fún afẹ́fẹ́, ó sì fiòṣùwọ̀n wọ̀n omi.
26. Nígbà tí ó pàsẹ fún òjò, tí ó sì laọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
27. Nígbà náà ni órí i, ó sì sọ ọ́ jáde;ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
28. Àti fún ènìyàn ni ó wí pé,‘Kíyè sí i ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n, àtiláti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.’ ”