30. Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ṣíbẹ̀ṣíbẹ̀ ìwọ àti àwọn ìjòyè rẹ kò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run.”
31. (Òwú àti ọkà báálì sí bàjẹ́ ni ìwọ̀n ìgbà ti wọn so ṣùgbọ́n ti ọkà-báálì kò lajú ti òwú kò sì là.
32. Onírúurú ọkà-wíìtì (jéró àti sípélítì) kò bàjẹ́, èṣo wọn padà gbó nítorí wọ́n máa ń pẹ so.)
33. Nígbà náà ni Mósè kúrò ni iwájú Fáráò, ó kúrò ni àárin ìgboro kọjá lọ sí ẹ̀yìn odi ìlú, ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí Olúwa, sísán àrá àti òjò yìnyín ti ń rọ̀ sì dáwọ́ dúró, òjò kò sì rọ̀ sí orí ilẹ̀ mọ́.
34. Nígbà tí Fáráò rí i pé òjò àti yìnyín àti àrá ti ń sán ti dáwọ́ dúró, ó tún ṣè ní ẹ̀ẹ̀kan sí i. Ọkan Fáráò àti àwọn ìjòyè rẹ̀ yigbì.
35. Ọkàn Fáráò sì yigbì, kò sì jẹ́ kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ó lọ, bí Olúwa ti sọ láti ẹnu Mósè.