21. Mósè gbà láti dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin náà, ẹni tí o fi Sípórà, ọmọbìnrin rẹ̀ fún Mósè láti fi ṣe aya.
22. Ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Gésómù, ó wí pé “Èmi ń ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì.”
23. Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ọba Éjíbítì kú. Àwọn ará Ísírẹ́lì ń kérora ní oko ẹrú wọn, wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ nítorí oko ẹrú tí wọ́n wà, igbe wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
24. Ọlọ́run gbọ́ igbe wọn, ó sì rántí Májẹ̀mu rẹ̀ pẹ̀lú Ábúráhámù, Ísáákì àti pẹ̀lú Jákọ́bù.
25. Nítorí náà, Ọlọ́run bojú wo àwọn ará Ísírẹ́lì, Ó sì wà láti gbà wọ́n sílẹ̀.