33. Nígbà náà ni Mósè sọ fún Árónì pe, “Mú ìkòkò kan, kí o sì kó mánà tí ó kún òṣùnwọ̀n ómérì kan sí inú rẹ̀, kí o sì gbé e kalẹ̀ ni iwájú Olúwa láti tọ́jú rẹ̀ pamọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀.”
34. Bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mósè, Árónì gbé mánà sí iwájú ẹ̀rí láti pa á mọ́.
35. Àwọn ará Ísírẹ́lì jẹ mánà fún ogójì ọdún títí wọ́n fi dé ilẹ̀ Kénánì ni ibi ti èso ti wà fún wọn láti jẹ; Wọ́n jẹ mánà títí tí wọ́n fi dé ilẹ̀ agbégbé Kénánì.
36. (Ọ̀sùnwọn ómérì kan sì jẹ́ ìdákan nínú ìdá-mẹ́wàá éfà.)