2. Rúbẹ́nì, Símónì, Léfì àti Júdà,
3. Ísákárì, Ṣébúlúnì àti Bẹ́ńjámínì,
4. Dánì àti Náfítalì, Gádì àti Ásérì.
5. Àwọn ìran Jákọ́bù sì jẹ́ àádọ́rin ní àpapọ̀; Jóṣẹ́fù sì ti wà ní Éjíbítì.
6. Wáyìí o, Jóṣẹ́fù àti gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìran náà kú,
7. Ṣùgbọ́n àwọn ará Ísírẹ́lì ń bí sí i, wọ́n ń pọ̀ sí i gidigidi, wọ́n kò sì ní òǹkà tí ó fi jẹ́ pé wọ́n kún ilẹ̀ náà.
8. Nígbà náà ni ọba túntún ti kò mọ nípa Jósẹ́fù jẹ ní ilẹ̀ Éjíbítì.
9. Ó sọ fún àwọn ènìyàn rẹ̀ “Ẹ wò ó, àwọn ará Ísírẹ́lì ti pọ̀ ní iye àti agbára jù fún wa.