32. Nítorí láti Jérúsálẹ́mù ni àwọn àṣẹ́kù yóò ti wá,àti láti òkè Ṣíhónì ni ikọ̀ àwọn tí ó sálà.Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
33. “Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọba Ásíríà:“Òun kì yóò wọ ìlú yìí wátàbí ta ẹyọ ọfà kan níhìn-ínÒun kì yóò wá síwájúu rẹ pẹ̀lú asàtàbí kí ó kó dágunró sílẹ̀ fún un.
34. Nípa ọ̀nà tí ó gbàwá náà ni yóò padà lọ;òun kì yóò wọ inú ìlú yìí,”ni Olúwa wí.
35. “Èmi yóò dáàbò bo ìlú yìí èmi ó sì gbàá là,nítorí mi àti nítoríì Dáfídì ìránṣẹ́ mi!”