21. Nitorina, Oluwa gbọ́ eyi, o binu: bẹ̃ni iná ràn ni Jakobu, ibinu si ru ni Israeli;
22. Nitori ti nwọn kò gbà Ọlọrun gbọ́, nwọn kò si gbẹkẹle igbala rẹ̀.
23. O paṣẹ fun awọsanma lati òke wá, o si ṣi ilẹkùn ọrun silẹ.
24. O si rọ̀jo Manna silẹ fun wọn ni jijẹ, o si fun wọn li ọkà ọrun.
25. Enia jẹ onjẹ awọn angeli; o rán onjẹ si wọn li ajẹyo.
26. O mu afẹfẹ ìla-õrun fẹ li ọrun, ati nipa agbara rẹ̀ o mu afẹfẹ gusu wá.
27. O rọ̀jo ẹran si wọn pẹlu bi erupẹ ilẹ, ati ẹiyẹ abiyẹ bi iyanrin okun.
28. O si jẹ ki o bọ́ si ãrin ibudo wọn, yi agọ wọn ka.