Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

O. Daf 26:1-11 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. ṢE idajọ mi, Oluwa; nitori ti mo ti nrìn ninu ìwa titọ mi; emi ti gbẹkẹle Oluwa pẹlu; njẹ ẹsẹ mi kì yio yẹ̀.

2. Wadi mi, Oluwa, ki o si ridi mi; dán inu mi ati ọkàn mi wò.

3. Nitoriti iṣeun-ifẹ rẹ mbẹ niwaju mi: emi si ti nrìn ninu otitọ rẹ.

4. Emi kò ba ẹni asan joko, bẹ̃li emi kì yio ba awọn alayidayida wọle.

5. Emi ti korira ijọ awọn oluṣe-buburu; emi kì yio si ba awọn enia buburu joko.

6. Emi o wẹ̀ ọwọ mi li ailẹṣẹ: bẹ̃li emi o si yi pẹpẹ rẹ ká, Oluwa.

7. Ki emi ki o le fi ohùn ọpẹ rò kalẹ, ti emi o si ma sọ̀rọ gbogbo iṣẹ iyanu rẹ.

8. Oluwa, emi ti nfẹ ibujoko ile rẹ, ibi agọ ọlá rẹ.

9. Máṣe kó ọkàn mi pọ̀ pẹlu awọn ẹlẹṣẹ, tabi ẹmi mi pẹlu awọn enia-ẹ̀jẹ.

10. Li ọwọ ẹniti ìwa-ìka mbẹ, ọwọ ọtún wọn si kún fun abẹtẹlẹ.

11. Ṣugbọn bi o ṣe ti emi, emi o ma rìn ninu ìwatitọ mi: rà mi pada, ki o si ṣãnu fun mi.

Ka pipe ipin O. Daf 26