Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

O. Daf 119:45-53 Yorùbá Bibeli (YCE)

45. Bẹ̃li emi o ma rìn ni alafia; nitori ti mo wá ẹkọ́ rẹ.

46. Emi o si ma sọ̀rọ ẹri rẹ niwaju awọn ọba, emi kì yio si tiju.

47. Emi o si ma ṣe inu-didùn ninu aṣẹ rẹ, ti emi ti fẹ.

48. Ọwọ mi pẹlu li emi o gbe soke si aṣẹ rẹ, ti emi ti fẹ; emi o si ma ṣe Ìṣàrò-ìlànà rẹ.

49. Ranti ọ̀rọ nì si ọmọ-ọdọ rẹ, ninu eyiti iwọ ti mu mi ṣe ireti.

50. Eyi ni itunu mi ninu ipọnju mi: nitori ọ̀rọ rẹ li o sọ mi di ãye.

51. Awọn agberaga ti nyọ-ṣuti si mi gidigidi: sibẹ emi kò fa sẹhin kuro ninu ofin rẹ.

52. Oluwa, emi ranti idajọ atijọ; emi si tu ara mi ninu.

53. Mo ni ibinujẹ nla nitori awọn enia buburu ti o kọ̀ ofin rẹ silẹ.

Ka pipe ipin O. Daf 119