Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

O. Daf 119:12-27 Yorùbá Bibeli (YCE)

12. Olubukún ni iwọ, Oluwa: kọ́ mi ni ilana rẹ.

13. Ẹnu mi li emi fi nsọ gbogbo idajọ ẹnu rẹ.

14. Emi ti nyọ̀ li ọ̀na ẹri rẹ, bi lori oniruru ọrọ̀.

15. Emi o ma ṣe àṣaro ninu ẹkọ́ rẹ emi o si ma juba ọ̀na rẹ.

16. Emi o ma ṣe inu-didùn ninu ilana rẹ: emi kì yio gbagbe ọ̀rọ rẹ.

17. Fi ọ̀pọlọpọ ba iranṣẹ rẹ ṣe, ki emi ki o le wà lãye, ki emi ki o le ma pa ọ̀rọ rẹ mọ́.

18. Là mi li oju, ki emi ki o le ma wò ohun iyanu wọnni lati inu ofin rẹ.

19. Alejo li emi li aiye: máṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fun mi.

20. Aiya mi bù nitori ifojusọna si idajọ rẹ nigbagbogbo.

21. Iwọ ti ba awọn agberaga wi, ti a ti fi gégun, ti o ti ṣina kuro nipa aṣẹ rẹ.

22. Mu ẹ̀gan ati àbuku kuro lara mi; nitoriti emi ti pa ẹri rẹ mọ́.

23. Awọn ọmọ-alade joko pẹlu, nwọn nsọ̀rọ mi: ṣugbọn iranṣẹ rẹ nṣe àṣaro ninu ilana rẹ:

24. Ẹri rẹ pẹlu ni didùn-inu mi ati ìgbimọ mi.

25. Ọkàn mi lẹ̀ mọ́ erupẹ: iwọ sọ mi di ãye gẹgẹ bi ọ̀rọ rẹ.

26. Emi ti rohin ọ̀na mi, iwọ si gbohùn mi: mã kọ́ mi ni ilana rẹ.

27. Mu oye ọ̀na ẹkọ́ rẹ ye mi: bẹ̃li emi o ma ṣe aṣaro iṣẹ iyanu rẹ.

Ka pipe ipin O. Daf 119