18. Ẹsẹ ẹniti nwọn fi ṣẹkẹṣẹkẹ pa lara: a dè e ninu irin:
19. Titi igba ti ọ̀rọ rẹ̀ de: ọ̀rọ Oluwa dan a wò.
20. Ọba ranṣẹ, nwọn si tú u silẹ; ani ijoye awọn enia, o si jọwọ rẹ̀ lọwọ lọ.
21. O fi jẹ oluwa ile rẹ̀, ati ijoye gbogbo ini rẹ̀.
22. Lati ma ṣe akoso awọn ọmọ-alade rẹ̀ nipa ifẹ rẹ̀; ati lati ma kọ́ awọn igbimọ rẹ̀ li ọgbọ́n.
23. Israeli si wá si Egipti pẹlu; Jakobu si ṣe atipo ni ilẹ Hamu.
24. O si mu awọn enia rẹ̀ bi si i pipọ̀-pipọ̀; o si mu wọn lagbara jù awọn ọta wọn lọ.
25. O yi wọn li aiya pada lati korira awọn enia rẹ̀, lati ṣe arekereke si awọn iranṣẹ rẹ̀.
26. O rán Mose iranṣẹ rẹ̀; ati Aaroni, ẹniti o ti yàn.
27. Nwọn fi ọ̀rọ àmi rẹ̀ hán ninu wọn, ati iṣẹ iyanu ni ilẹ Hamu.
28. O rán òkunkun, o si mu u ṣú; nwọn kò si ṣaigbọran si ọ̀rọ rẹ̀.
29. O sọ omi wọn di ẹ̀jẹ, o si pa ẹja wọn.
30. Ilẹ wọn mu ọ̀pọlọ jade wá li ọ̀pọlọpọ, ni iyẹwu awọn ọba wọn.
31. O sọ̀rọ, oniruru eṣinṣin si de, ati ina-aṣọ ni gbogbo agbegbe wọn.
32. O fi yinyin fun wọn fun òjo, ati ọwọ iná ni ilẹ wọn.
33. O si lu àjara wọn, ati igi ọ̀pọtọ wọn; o si dá igi àgbegbe wọn.
34. O sọ̀rọ, eṣú si de ati kokoro li ainiye.