Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Mal 2:2-10 Yorùbá Bibeli (YCE)

2. Bi ẹnyin kì o ba gbọ́, ti ẹnyin kì o ba fi si aiya, lati fi ogo fun orukọ mi, li Oluwa awọn ọmọ-ogun wi; emi o si rán egún si ori nyin, emi o si fi ibukun nyin ré, lõtọ mo ti fi ré na, nitori pe, ẹnyin kò fi i si ọkàn.

3. Wò o, emi o ba irugbìn nyin jẹ, emi o si fi igbẹ́ rẹ́ nyin loju, ani igbẹ́ asè ọ̀wọ nyin wọnni; a o si kó nyin lọ pẹlu rẹ̀.

4. Ẹnyin o si mọ̀ pe, emi li o ti rán ofin yi si nyin, ki majẹ̀mu mi le wà pẹlu Lefi, li Oluwa awọn ọmọ-ogun wi.

5. Majẹmu mi ti iyè on alafia wà pẹlu rẹ̀; mo si fi wọn fun u, nitori bibẹ̀ru ti o bẹ̀ru mi, ti ẹ̀ru orukọ mi si bà a.

6. Ofin otitọ wà li ẹnu rẹ̀, a kò si ri ìwa-buburu li etè rẹ̀: o ba mi rìn li alafia ati ni ododo, o si yi ọ̀pọlọpọ kuro ninu ìwa-buburu.

7. Nitori ète alufa iba ma pa ìmọ mọ, ki nwọn ki o si ma wá ofin li ẹnu rẹ̀: nitori onṣẹ Oluwa awọn ọmọ-ogun li on iṣe.

8. Ṣugbọn ẹnyin ti yapa kuro li ọ̀na na: ẹnyin ti mu ọ̀pọlọpọ kọsẹ ninu ofin; ẹnyin ti ba majẹmu Lefi jẹ, li Oluwa awọn ọmọ-ogun wi.

9. Nitorina li emi pẹlu ṣe sọ nyin di ẹ̀gan, ati ẹni aikàsi niwaju gbogbo enia, niwọ̀n bi ẹnyin kò ti pa ọ̀na mi mọ, ti ẹnyin si ti nṣe ojusaju ninu ofin.

10. Baba kanna ki gbogbo wa ha ni? Ọlọrun kanna kó ha da wa bi? nitori kili awa ha ṣe nhùwa arekerekè olukuluku si arakunrin rẹ̀, nipa sisọ majẹmu awọn baba wa di alaimọ́.

Ka pipe ipin Mal 2