Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jer 40:1-3 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. Ọ̀RỌ ti o tọ̀ Jeremiah wá lati ọdọ Oluwa, lẹhin ti Nebusaradani, balogun iṣọ, ti ranṣẹ pè e lati Rama. Nitori nigbati o mu u, a fi ẹwọn dè e lãrin gbogbo awọn igbekun Jerusalemu ati Juda, ti a kó ni ìgbekun lọ si Babeli.

2. Balogun iṣọ si mu Jeremiah, o si wi fun u pe, Oluwa, Ọlọrun rẹ, ti sọ ibi yi si ilu yi.

3. Oluwa si ti mu u wá, o si ṣe gẹgẹ bi o ti wi: nitoripe ẹnyin ti ṣẹ̀ si Oluwa, ẹ kò si gbọ́ ohùn rẹ̀, nitorina ni nkan yi ṣe de ba nyin.

Ka pipe ipin Jer 40