Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jer 26:18-24 Yorùbá Bibeli (YCE)

18. Mikah, ara Moraṣi, ṣe woli li ọjọ Hesekiah, ọba Juda, o si wi fun gbogbo enia Juda pe: Bayi li Oluwa awọn ọmọ-ogun wi: a o tulẹ Sioni fun oko, Jerusalemu yio di òkiti alapa, ati oke ile yi gẹgẹ bi ibi giga igbo.

19. Njẹ, Hesekiah, ọba Juda, ati gbogbo Juda ha pa a bi? Ẹ̀ru Oluwa kò ha bà a, kò ha bẹ Oluwa bi? Oluwa si yi ọkàn pada niti ibi ti o ti sọ si wọn; Bayi li awa iba ṣe mu ibi nla wá sori ẹmi wa?

20. Ọkunrin kan si wà ẹ̀wẹ, ti o sọ asọtẹlẹ ni orukọ Oluwa, ani Urijah, ọmọ Ṣemaiah, ara Kirjatjearimu, ti o sọ asọtẹlẹ si ilu yi, ati si ilẹ yi, gẹgẹ bi gbogbo ọ̀rọ Jeremiah.

21. Ati nigbati Jehoiakimu, ọba, pẹlu gbogbo ọkunrin alagbara rẹ̀, ati awọn ijoye gbọ́ ọ̀rọ rẹ̀, ọba nwá a lati pa; ṣugbọn nigbati Urijah gbọ́, o bẹ̀ru, o salọ o si wá si Egipti.

22. Jehoiakimu, ọba, si rán enia lọ si Egipti, ani Elnatani, ọmọ Akbori ati enia miran pẹlu rẹ̀ lọ si Egipti.

23. Nwọn si mu Urijah lati Egipti tọ Jehoiakimu ọba wá; ẹni ti o fi idà pa a, o si sọ okú rẹ̀ sinu isa-okú awọn enia lasan.

24. Bẹ̃ni ọwọ Ahikamu, ọmọ Safani mbẹ pẹlu Jeremiah, ki nwọn ki o má ba fi i le awọn enia lọwọ lati pa.

Ka pipe ipin Jer 26