Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Isa 19:9-21 Yorùbá Bibeli (YCE)

9. Pẹlupẹlu awọn ti nṣiṣẹ ọ̀gbọ daradara, ati awọn ti nwun asọ-àla yio dãmu.

10. A o si fọ́ wọn ni ipilẹ rẹ̀, gbogbo awọn alagbàṣe li a o bà ni inu jẹ.

11. Nitõtọ òpe ni awọn ọmọ-alade Soani, ìmọ awọn ìgbimọ ọlọgbọn Farao di wère: ẹ ha ti ṣe sọ fun Farao, pe, Emi li ọmọ ọlọgbọn, ọmọ awọn ọba igbãni?

12. Awọn dà? awọn ọlọgbọn rẹ dà? si jẹ ki wọn sọ fun ọ nisisiyi, si jẹ ki wọn mọ̀ ete ti Oluwa awọn ọmọ-ogun ti pa le Egipti.

13. Awọn ọmọ-alade Soani di aṣiwère, a tàn awọn ọmọ-alade Nofi jẹ; ani awọn ti iṣe pataki ẹyà rẹ̀.

14. Oluwa ti mí ẽmi iyapa si inu rẹ̀ na: nwọn si ti mu Egipti ṣina ninu gbogbo iṣẹ inu rẹ̀, gẹgẹ bi ọ̀muti enia ti nta gbọngbọ́n ninu ẽbi rẹ̀.

15. Bẹ̃ni kì yio si iṣẹkiṣẹ́ fun Egipti, ti ori tabi ìru, ẹka tabi oko-odò, le ṣe.

16. Li ọjọ na ni Egipti yio dabi obinrin; yio si warìri, ẹ̀ru yio si bà a nitori mimì ọwọ́ Oluwa awọn ọmọ-ogun ti o mì le e lori.

17. Ilẹ Juda yio si di ẹ̀ru fun Egipti, olukuluku ẹniti o dá a sọ ninu rẹ̀ yio tikararẹ̀ bẹ̀ru, nitori ìmọ Oluwa awọn ọmọ-ogun, ti o ti gbà si i.

18. Li ọjọ na ni ilu marun ni ilẹ Egipti yio fọ̀ ède Kenaani, ti nwọn o sì bura si Oluwa awọn ọmọ-ogun; a o ma pè ọkan ni Ilu ìparun.

19. Li ọjọ na ni pẹpẹ kan yio wà fun Oluwa li ãrin ilẹ Egipti, ati ọwọ̀n ni àgbegbe inu rẹ̀ fun Oluwa.

20. Yio si jẹ fun ami, ati fun ẹ̀ri si Oluwa awọn ọmọ-ogun ni ilẹ Egipti: nitori nwọn o kigbe pè Oluwa nitori awọn aninilara, yio si rán olugbala kan si i, ati ẹni-nla, on o si gbà wọn.

21. Oluwa yio si di mimọ̀ fun Egipti, awọn ara Egipti yio so mọ́ Oluwa li ọjọ na, nwọn o si rú ẹbọ, nwọn o si ta ọrẹ; nitõtọ nwọn o jẹ'jẹ fun Oluwa, nwọn o si mu u ṣẹ.

Ka pipe ipin Isa 19