Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2. Kro 21:4-12 Yorùbá Bibeli (YCE)

4. Nigbati Jehoramu si dide si ijọba baba rẹ̀, o mu ara rẹ̀ le, o si fi idà pa gbogbo awọn arakunrin rẹ̀, ati ninu awọn ijoye Israeli.

5. Jehoramu jẹ ẹni ọdun mejilelọgbọ̀n nigbati o bẹ̀rẹ si ijọba, o si jọba li ọdun mẹjọ ni Jerusalemu.

6. O si rìn li ọ̀na awọn ọba Israeli, gẹgẹ bi ile Ahabu ti ṣe: nitoriti o ni ọmọbinrin Ahabu li aya: o si ṣe eyiti o buru li oju Oluwa.

7. Ṣugbọn Oluwa kò fẹ ipa ile Dafidi run, nitori majẹmu ti o ti ba Dafidi da, ati bi o ti ṣe ileri lati fun u ni imọlẹ kan ati fun awọn ọmọ rẹ̀ lailai.

8. Li ọjọ rẹ̀ li awọn ara Edomu ṣọ̀tẹ kuro labẹ ọwọ Juda, nwọn si jẹ ọba fun ara wọn.

9. Nigbana ni Jehoramu rekọja lọ pẹlu awọn ijoye rẹ̀, ati gbogbo kẹkẹ́ rẹ̀ pẹlu rẹ̀: o si dide li oru, o si kọlù awọn ara Edomu ti o ká a mọ, ati awọn olori kẹkẹ́.

10. Sibẹ awọn ara Edomu ṣọ̀tẹ kuro labẹ ọwọ Juda, titi di oni yi. Akokò na pẹlu ni Libna ṣọ̀tẹ kuro labẹ ọwọ rẹ̀; nitoriti o ti kọ̀ Oluwa, Ọlọrun awọn baba rẹ̀ silẹ.

11. Pẹlupẹlu o ṣe ibi giga wọnni lori òke Judah, o si mu ki awọn olugbe Jerusalemu ki o ṣe àgbere, o si mu Juda ṣẹ̀.

12. Iwe kan si ti ọdọ Elijah, woli, wá si ọdọ rẹ̀ wipe: Bayi li Oluwa, Ọlọrun Dafidi baba rẹ wi, nitoriti iwọ kò rìn li ọ̀na Jehoṣafati, baba rẹ, tabi li ọ̀na Asa, ọba Juda;

Ka pipe ipin 2. Kro 21