Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2. Kro 21:17-20 Yorùbá Bibeli (YCE)

17. Nwọn si gòke wá si Juda, nwọn si ya wọle, nwọn si kó gbogbo ọrọ̀ ti a ri ni ile ọba ati awọn ọmọ rẹ̀ pẹlu, ati awọn obinrin rẹ̀, ni igbekun lọ; tobẹ̃ ti a kò ṣẹ́ku ọkunrin kan silẹ fun u, bikòṣe Jehoahasi, abikẹhin ninu awọn ọmọ rẹ̀.

18. Lẹhin gbogbo eyi Oluwa fi àrun, ti a kò le wòsan, kọlù u ni ifun.

19. O si ṣe bẹ̃ bi akokò ti nlọ ati lẹhin ọdun meji, ni ifun rẹ̀ tu jade nitori aìsan rẹ̀, o si kú ninu irora buburu na: awọn enia rẹ̀ kò si ṣe ijona fun u gẹgẹ bi ijona ti awọn baba rẹ̀.

20. Ẹni ọdun mejilelọgbọn ni nigbati o bẹ̀rẹ si ijọba, o si jọba ọdun mẹjọ ni Jerusalemu, o si fi ilẹ silẹ laiwu ni: nwọn si sìn i ni ilu Dafidi; ṣugbọn kì iṣe ninu iboji awọn ọba.

Ka pipe ipin 2. Kro 21