Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Romu 9:26-30 BIBELI MIMỌ (BM)

26. Ní ibìkan náà tí a ti sọ fún wọn rí pé,‘Ẹ kì í ṣe eniyan mi mọ́’ni a óo ti pè wọ́n níọmọ Ọlọrun alààyè.”

27. Aisaya náà kéde nípa Israẹli pé, “Bí àwọn ọmọ Israẹli tilẹ̀ pọ̀ bí iyanrìn òkun, sibẹ díẹ̀ péré ni a óo gbà là.

28. Nítorí ṣókí ati wéré wéré ni ìdájọ́ Ọlọrun yóo jẹ́ lórí ilẹ̀ ayé.”

29. Ṣiwaju eléyìí, Aisaya sọ bákan náà pé, “Bíkòṣe pé Oluwa alágbára jùlọ dá díẹ̀ sí ninu àwọn ọmọ wa ni, bíi Sodomu ni à bá rí, à bá sì dàbí Gomora.”

30. Kí ni èyí já sí? Ó já sí pé àwọn orílẹ̀-èdè tí kò bìkítà rárá láti wá ojurere Ọlọrun, àwọn náà gan-an ni Ọlọrun wá dá láre, ó dá wọn láre nítorí wọ́n gbàgbọ́;

Ka pipe ipin Romu 9