Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Matiu 5:3-13 BIBELI MIMỌ (BM)

3. “Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ó jẹ́ òtòṣì ní ẹ̀mí,nítorí tiwọn ni ìjọba ọ̀run.

4. Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀,nítorí Ọlọrun yóo tù wọ́n ninu.

5. Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn onírẹ̀lẹ̀,nítorí wọn yóo jogún ayé.

6. Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ebi òdodo ń pa, tí òùngbẹ òdodo sì ń gbẹ,nítorí Ọlọrun yóo bọ́ wọn ní àbọ́yó.

7. Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn aláàánú,nítorí Ọlọrun yóo ṣàánú wọn.

8. Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ọkàn wọn mọ́,nítorí wọn yóo rí Ọlọrun.

9. Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ó ń mú kí alaafia wà láàrin àwọn eniyan,nítorí Ọlọrun yóo pè wọ́n ní ọmọ rẹ̀.

10. Ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí eniyan ń ṣe inúnibíni sí nítorí òdodo,nítorí tiwọn ni ìjọba ọ̀run.

11. “Ayọ̀ ń bẹ fun yín, tí wọ́n bá kẹ́gàn yín, tí wọ́n ṣe inúnibíni si yín, tí wọ́n bá ń fi èké sọ ọ̀rọ̀ burúkú lóríṣìíríṣìí si yín nítorí mi.

12. Ẹ máa yọ̀, kí inú yín máa dùn, nítorí èrè yín pọ̀ ní ọ̀run. Nítorí bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe inúnibíni sí àwọn wolii tí ó ti wà ṣiwaju yín.

13. “Ẹ̀yin ni iyọ̀ ayé; ṣugbọn bí iyọ̀ bá di òbu, kí ni yóo tún sọ ọ́ di iyọ̀ gidi mọ́? Kò wúlò fún ohunkohun mọ́ àfi kí á dà á nù, kí eniyan máa tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀.

Ka pipe ipin Matiu 5