Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Luku 2:28-35 BIBELI MIMỌ (BM)

28. Ni Simeoni bá gbé ọmọ náà lọ́wọ́, ó yin Ọlọrun lógo, ó ní,

29. “Nisinsinyii, Oluwa, dá ọmọ-ọ̀dọ̀ rẹ sílẹ̀ ní alaafia,gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.

30. Nítorí ojú mi ti rí ìgbàlà rẹ,

31. tí o ti pèsè níwájú gbogbo eniyan;

32. ìmọ́lẹ̀ láti fi ọ̀nà han àwọn kèfèríati ògo fún Israẹli, eniyan rẹ.”

33. Ẹnu ya baba ati ìyá Jesu nítorí ohun tí ó sọ nípa rẹ̀.

34. Simeoni wá súre fún wọn. Ó sọ fún Maria ìyá rẹ̀ pé, “A gbé ọmọ yìí dìde fún ìṣubú ati ìdìde ọpọlọpọ ní Israẹli ati bí àmì tí àwọn eniyan yóo kọ̀.

35. Nítorí yóo mú kí àṣírí èrò ọkàn ọpọlọpọ di ohun tí gbogbo eniyan yóo mọ̀. Ìbànújẹ́ yóo sì gún ọ ní ọkàn bí idà.”

Ka pipe ipin Luku 2