27. Ẹ̀mí wá darí rẹ̀ sí Tẹmpili ní àkókò tí àwọn òbí ọmọ náà gbé e wá, láti ṣe gbogbo ètò tí ó yẹ gẹ́gẹ́ bí òfin.
28. Ni Simeoni bá gbé ọmọ náà lọ́wọ́, ó yin Ọlọrun lógo, ó ní,
29. “Nisinsinyii, Oluwa, dá ọmọ-ọ̀dọ̀ rẹ sílẹ̀ ní alaafia,gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
30. Nítorí ojú mi ti rí ìgbàlà rẹ,
31. tí o ti pèsè níwájú gbogbo eniyan;
32. ìmọ́lẹ̀ láti fi ọ̀nà han àwọn kèfèríati ògo fún Israẹli, eniyan rẹ.”