Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Luku 18:36-41 BIBELI MIMỌ (BM)

36. Nígbà tí ó gbọ́ tí ọ̀pọ̀ eniyan ń kọjá lọ, ó wádìí ohun tí ó dé.

37. Wọ́n sọ fún un pé, “Jesu ará Nasarẹti ní ń kọjá.”

38. Ni alágbe náà bá pariwo pé, “Jesu, ọmọ Dafidi, ṣàánú mi!”

39. Àwọn tí ó ń kọjá lọ ń bá a wí pé kí ó panu mọ́. Ṣugbọn ńṣe ni ó túbọ̀ ń kígbe pé, “Ọmọ Dafidi, ṣàánú mi.”

40. Jesu bá dúró, ó ní kí wọ́n lọ fà á lọ́wọ́ wá sọ́dọ̀ òun. Nígbà tí ó dé, Jesu bi í pé,

41. “Kí ni o fẹ́ kí n ṣe fún ọ?”Ó dáhùn pé, “Alàgbà, mo fẹ́ tún ríran ni!”

Ka pipe ipin Luku 18