Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Luku 1:50-58 BIBELI MIMỌ (BM)

50. àánú rẹ̀ sì wà láti ìran dé ìranfún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.

51. Ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ fi agbára rẹ̀ hàn,ó tú àwọn tí ó gbéraga ninu ọkàn wọn ká.

52. Ó yọ àwọn ìjòyè kúrò lórí oyè,ó gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ga.

53. Ó fi oúnjẹ tí ó dára bọ́ àwọn tí ebi ń pa,ó mú àwọn ọlọ́rọ̀ jáde lọ́wọ́ òfo.

54. Ó ran Israẹli ọmọ-ọ̀dọ̀ rẹ̀ lọ́wọ́nígbà tí ó ranti àánú rẹ̀,

55. gẹ́gẹ́ bí ìlérí tí ó ti ṣe fún àwọn baba wa:fún Abrahamu ati fún ìdílé rẹ̀ títí lae.”

56. Maria dúró lọ́dọ̀ Elisabẹti tó bíi oṣù mẹta, ó bá pada lọ sí ilé rẹ̀.

57. Nígbà tí àkókò Elisabẹti tó tí yóo bí, ó bí ọmọkunrin kan.

58. Àwọn aládùúgbò rẹ̀ ati àwọn mọ̀lẹ́bí rẹ̀ gbọ́ pé Oluwa ti ṣàánú pupọ fún un, wọ́n wá bá a yọ̀.

Ka pipe ipin Luku 1