Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Johanu 18:3-8 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Judasi bá mú àwọn ọmọ-ogun ati àwọn ẹ̀ṣọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn olórí alufaa ati àwọn Farisi, wọ́n wá sibẹ pẹlu ògùṣọ̀ ati àtùpà ati àwọn ohun ìjà.

4. Nígbà tí Jesu rí ohun gbogbo tí yóo ṣẹlẹ̀ sí òun, ó jáde lọ pàdé wọn, ó bi wọ́n pé, “Ta ni ẹ̀ ń wá?”

5. Wọ́n dá a lóhùn pé, “Jesu ará Nasarẹti ni.”Ó sọ fún wọn pé, “Èmi gan-an nìyí.”Judasi, ẹni tí ó fi lé àwọn ọ̀tá lọ́wọ́, dúró pẹlu wọn.

6. Nígbà tí ó sọ fún wọn pé, “Èmi gan-an nìyí,” wọ́n bì sẹ́yìn, ni wọ́n bá ṣubú lulẹ̀.

7. Ó tún bi wọ́n pé, “Ta ni ẹ̀ ń wá?”Wọ́n dáhùn pé, “Jesu ará Nasarẹti ni.”

8. Jesu wí fún wọn pé, “Mo sọ fun yín pé èmi gan-an nìyí. Bí ó bá jẹ́ pé èmi ni ẹ̀ ń wá, ẹ jẹ́ kí àwọn wọnyi máa lọ.”

Ka pipe ipin Johanu 18