Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Heberu 1:1-10 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ní ìgbà àtijọ́, oríṣìíríṣìí ọ̀nà ni Ọlọrun fi ń bá àwọn baba wa sọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wolii rẹ̀.

2. Ní àkókò ìkẹyìn yìí, ó wá bá wa sọ̀rọ̀ nípasẹ̀ Ọmọ rẹ̀, ẹni tí ó fi ṣe àrólé ohun gbogbo, nípasẹ̀ ẹni tí ó dá ayé.

3. Ọmọ yìí jẹ́ ẹni tí ògo Ọlọrun hàn lára rẹ̀, ó sì jẹ́ àwòrán bí Ọlọrun ti rí gan-an. Òun ni ó mú kí gbogbo nǹkan dúró nípa agbára ọ̀rọ̀ rẹ̀. Lẹ́yìn tí ó ti wẹ ẹ̀ṣẹ̀ eniyan nù tán, ó wá jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún Ọ̀gá Ògo ní ibi tí ó ga jùlọ.

4. Ó ní ipò tí ó ga ju ti àwọn angẹli lọ, gẹ́gẹ́ bí ó ti ní orúkọ tí ó ju tiwọn lọ.

5. Nítorí èwo ninu àwọn angẹli ni ó fi ìgbà kan sọ fún pé,“Ìwọ ni ọmọ mi,lónìí ni mo bí ọ?”Tabi tí ó sọ fún pé,“Èmi yóo jẹ́ baba fún un,òun náà yóo sì jẹ́ ọmọ fún mi?”

6. Ṣugbọn nígbà tí ó mú àkọ́bí rẹ̀ wọ inú ayé, ohun tí ó sọ ni pé,“Kí gbogbo àwọn angẹliỌlọrun foríbalẹ̀ fún un.”

7. Ohun tí ó sọ nípa àwọn angẹli ni pé,“Ẹni tí ó ṣe àwọn angẹli rẹ̀ ní ẹ̀fúùfù,tí ó ṣe àwọn òjíṣẹ́ rẹ̀ ní ọwọ́ iná.”

8. Ṣugbọn ohun tí ó sọ fún Ọmọ náà ni pé,“Ìfẹ́ rẹ wà títí laelae, Ọlọrun,ọ̀pá òtítọ́ ni ọ̀pá ìjọba rẹ.

9. O fẹ́ràn òdodo, o kórìíra ẹ̀ṣẹ̀.Nítorí èyí, Ọlọrun, àní Ọlọrun rẹ, fi òróró yàn ọ́láti gbé ọ ga ju àwọn ẹgbẹ́ rẹ lọ.”

10. Ó tún sọ pé,“O ti wà láti ìṣẹ̀dálẹ̀ ayé, Oluwa,ìwọ ni o fi ìpìlẹ̀ ayé lélẹ̀.Iṣẹ́ ọwọ́ rẹ ni àwọn ọ̀run.

Ka pipe ipin Heberu 1