25. Hagari ni òkè Sinai ní Arabia tíí ṣe àpẹẹrẹ Jerusalẹmu ti òní. Ó wà ninu ipò ẹrú pẹlu àwọn ọmọ rẹ̀.
26. Ṣugbọn Jerusalẹmu ti òkè wà ninu òmìnira. Òun ni ìyá wa.
27. Nítorí ó wà ní àkọsílẹ̀ pé,“Máa yọ̀, ìwọ àgàn tí kò bímọ rí.Sọ̀rọ̀ kí o kígbe sókè, ìwọ tí kò rọbí rí.Nítorí àwọn ọmọ àgàn pọ̀ ju ti obinrin tí ó ní ọkọ lọ.”
28. Ṣugbọn ẹ̀yin, ará, ọmọ ìlérí bíi Isaaki ni yín.