Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Samuẹli Keji 22:34-48 BIBELI MIMỌ (BM)

34. Ó fún ẹsẹ̀ mi lókun láti sáré bí àgbọ̀nrín,ó sì mú kí n wà ní àìléwu lórí àwọn òkè.

35. Ó kọ́ mi ní ogun jíjà,tóbẹ́ẹ̀ tí mo lè lo ọrun idẹ.

36. “O fún mi ní àpáta ìgbàlà rẹ,ìrànlọ́wọ́ rẹ ni ó sọ mí di ẹni ńlá.

37. Ìwọ ni o kò jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tá tẹ̀ mí,bẹ́ẹ̀ ni o kò jẹ́ kí ẹsẹ̀ mí kí ó yẹ̀.

38. Mo lépa àwọn ọ̀tá mi,mo sì ṣẹgun wọnn kò pada lẹ́yìn wọn títí tí mo fi pa wọ́n run.

39. Mo pa wọ́n run, mo bì wọ́n lulẹ̀;wọn kò sì lè dìde mọ́;wọ́n ṣubú lábẹ́ ẹsẹ̀ mi.

40. Ìwọ ni o fún mi lágbára láti jagun,o jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi rì lábẹ́ mi.

41. O mú kí àwọn ọ̀tá mi sá fún mi,mo sì pa àwọn tí wọ́n kórìíra mi run.

42. Wọ́n wá ìrànlọ́wọ́ káàkiri,ṣugbọn kò sí ẹni tí ó lè gbà wọ́n;wọ́n pe OLUWA,ṣugbọn kò dá wọn lóhùn.

43. Mo fọ́ wọn túútúú, wọ́n sì dàbí erùpẹ̀ ilẹ̀;mo tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀, wọ́n sì dàbí ẹrọ̀fọ̀ lójú títì.

44. “Ìwọ ni o gbà mí lọ́wọ́ ìjà àwọn eniyan mi,o sì mú kí ìjọba mi dúró lórí àwọn orílẹ̀ èdè;àwọn eniyan tí n kò mọ̀ rí di ẹni tí ó ń sìn mí.

45. Àwọn àjèjì ń wólẹ̀ níwájú mi,ẹsẹ̀kẹsẹ̀ tí wọ́n bá ti gbúròó mi, ni wọ́n ń mú àṣẹ mi ṣẹ.

46. Ẹ̀rù ba àwọn àjèjì,wọ́n gbọ̀n jìnnìjìnnì jáde ní ibi ààbò wọn.

47. “OLUWA wà láàyè,ìyìn ni fún àpáta ààbò mi.Ẹ gbé Ọlọrun mi ga,ẹni tíí ṣe àpáta ìgbàlà mi.

48. Ọlọrun ti jẹ́ kí n gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi,ó ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba lábẹ́ mi;

Ka pipe ipin Samuẹli Keji 22