Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Samuẹli Keji 22:27-36 BIBELI MIMỌ (BM)

27. Ọlọrun, mímọ́ ni ọ́, sí gbogbo àwọn tí wọ́n bá mọ́,ṣugbọn o kórìíra gbogbo àwọn eniyan burúkú.

28. Ò máa gba àwọn onírẹ̀lẹ̀,o dójú lé àwọn agbéraga, láti rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.

29. “OLUWA, ìwọ ni ìmọ́lẹ̀ mi,ìwọ ni o sọ òkùnkùn mi di ìmọ́lẹ̀.

30. Nípa agbára rẹ, mo lè ṣẹgun àwọn ọ̀tá mi,mo sì lè fo odi kọjá.

31. Ní ti Ọlọrun yìí, pípé ni ọ̀nà rẹ̀,òtítọ́ ni ìlérí OLUWA,ó sì jẹ́ apata fun gbogbo àwọn tí wọ́n bá sápamọ́ sábẹ́ ààbò rẹ̀.

32. Ta ni Ọlọrun bí kò ṣe OLUWA?Ta sì ni àpáta ààbò bí kò ṣe Ọlọrun wa?

33. Ọlọrun yìí ni ààbò mi tí ó lágbára,ó mú gbogbo ewu kúrò ní ọ̀nà mi.

34. Ó fún ẹsẹ̀ mi lókun láti sáré bí àgbọ̀nrín,ó sì mú kí n wà ní àìléwu lórí àwọn òkè.

35. Ó kọ́ mi ní ogun jíjà,tóbẹ́ẹ̀ tí mo lè lo ọrun idẹ.

36. “O fún mi ní àpáta ìgbàlà rẹ,ìrànlọ́wọ́ rẹ ni ó sọ mí di ẹni ńlá.

Ka pipe ipin Samuẹli Keji 22