Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Samuẹli Keji 22:21-27 BIBELI MIMỌ (BM)

21. “OLUWA fún mi ní èrè òdodo mi,ó san ẹ̀san fún mi, nítorí pé mo jẹ́ aláìlẹ́bi.

22. Nítorí pé mo pa àwọn òfin OLUWA mọ́,n kò sì ṣe agídí, kí n yipada kúrò lọ́dọ̀ Ọlọrun mi.

23. Mo ti tẹ̀lé gbogbo òfin rẹ̀,n kò sì ṣe àìgbọràn sí àwọn ìlànà rẹ̀.

24. N kò lẹ́bi níwájú rẹ̀,mo sì ti yẹra fún ẹ̀ṣẹ̀ dídá.

25. Nítorí náà ni OLUWA ṣe san án fún mi, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi,ati gẹ́gẹ́ bí mo ti jẹ́ mímọ́ níwájú rẹ̀.

26. “OLUWA, ò máa ṣe olóòótọ́ sí gbogbo àwọn tí wọ́n bá hu ìwà òtítọ́ sí ọ;ò sì máa fi ara rẹ hàn bí aláìlẹ́bi, fún gbogbo àwọn tí kò ní ẹ̀bi.

27. Ọlọrun, mímọ́ ni ọ́, sí gbogbo àwọn tí wọ́n bá mọ́,ṣugbọn o kórìíra gbogbo àwọn eniyan burúkú.

Ka pipe ipin Samuẹli Keji 22