Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Samuẹli Keji 22:10-20 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Ó tẹ àwọn ọ̀run ba, ó sì sọ̀kalẹ̀;ìkùukùu tí ó ṣókùnkùn sì wà ní abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.

11. Ó gun orí Kerubu, ó fò,afẹ́fẹ́ ni ó fi ṣe ìyẹ́ tí ó fi ń fò.

12. Ó fi òkùnkùn bo ara,ìkùukùu tí ó ṣókùnkùn,tí ó sì kún fún omi ni ó fi ṣe ìbòrí.

13. Ẹ̀yinná tí ń jó ń jáde,láti inú ìmọ́lẹ̀ tí ó wà níwájú rẹ̀.

14. “OLUWA sán ààrá láti ọ̀run wá,ayé sì gbọ́ ohùn ọ̀gá ògo.

15. Ó ta ọpọlọpọ ọfà, ó sì tú wọn ká.Ó tan mànàmáná, wọ́n sì ń sá.

16. Ìsàlẹ̀ òkun di gbangba, ìpìlẹ̀ ayé sì ṣí sílẹ̀,nígbà tí OLUWA bá wọn wí,tí ó sì fi ibinu jágbe mọ́ wọn.

17. “OLUWA nawọ́ sílẹ̀ láti òkè wá, ó dì mí mú,ó fà mí jáde kúrò ninu omi jíjìn.

18. Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi, tí ó lágbára;ati lọ́wọ́ gbogbo àwọn tí wọ́n kórìíra mi;nítorí pé wọ́n lágbára jù mí lọ.

19. Nígbà tí mo wà ninu ìpọ́njú; wọ́n gbógun tì mí,ṣugbọn OLUWA dáàbò bò mí.

20. Ó ràn mí lọ́wọ́,ó kó mi yọ ninu ewu,ó sì gbà mí là,nítorí pé inú rẹ̀ dùn sí mi.

Ka pipe ipin Samuẹli Keji 22