Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Solomoni 1:6-17 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Má wò mí tìka-tẹ̀gbin, nítorí pé mo dúdú,oòrùn tó pa mí ló ṣe àwọ̀ mi bẹ́ẹ̀.Àwọn ọmọ ìyá mi lọkunrin bínú sí mi,wọ́n fi mí ṣe olùtọ́jú ọgbà àjàrà,ṣugbọn n kò tọ́jú ọgbà àjàrà tèmi alára.

7. Sọ fún mi, ìwọ ẹni tí ọkàn mi fẹ́:níbo ni ò ó máa ń da àwọn ẹran rẹ lọ jẹko?Níbo ni wọ́n ti ń sinmi,nígbà tí oòrùn bá mú?Kí n má baà máa wá ọ kiri,láàrin agbo ẹran àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ?

8. Ìwọ tí o lẹ́wà jùlọ láàrin àwọn obinrin,bí o kò bá mọ ibẹ̀,ṣá máa tẹ̀lé ipa agbo ẹran.Jẹ́ kí àwọn ọmọ ẹran rẹ máa jẹkolẹ́bàá àgọ́ àwọn olùṣọ́-aguntan.

9. Olólùfẹ́ mi, mo fi ọ́ wé akọ ẹṣin tí ń fa kẹ̀kẹ́ ogun Farao.

10. Nǹkan ọ̀ṣọ́ mú kí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ lẹ́wà,ẹ̀gbà ọrùn sì mú kí ọrùn rẹ lẹ́wà.

11. A óo ṣe àwọn nǹkan ọ̀ṣọ́ wúrà,tí a fi fadaka ṣe ọnà sí lára fún ọ.

12. Nígbà tí ọba rọ̀gbọ̀kú lórí ìjókòó rẹ̀,turari mi ń tú òórùn dídùn jáde.

13. Olùfẹ́ mi dàbí àpò òjíá,bí ó ti sùn lé mi láyà.

14. Olùfẹ́ mi dàbí ìdì òdòdó igi Sipirẹsi,ninu ọgbà àjàrà Engedi.

15. Wò ó! O mà dára o, olólùfẹ́ mi;o lẹ́wà pupọ.Ojú rẹ tutù bíi ti àdàbà.

16. Háà, o mà dára o! Olùfẹ́ mi,o lẹ́wà gan-an ni.Ewéko tútù ni yóo jẹ́ ibùsùn wa.

17. Igi Kedari ni òpó ilé wa,igi firi sì ni ọ̀pá àjà ilé wa.

Ka pipe ipin Orin Solomoni 1