Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 9:1-7 BIBELI MIMỌ (BM)

1. OLUWA, tọkàntọkàn ni n óo fi dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ;n óo ròyìn gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ.

2. N óo yọ̀, inú mi yóo sì máa dùn nítorí rẹ;n óo kọ orin ìyìn orúkọ rẹ, ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.

3. Nígbà tí àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà,wọ́n ṣubú, wọ́n sì parun níwájú rẹ.

4. Nítorí ìwọ ni o fi ìdí ẹ̀tọ́ mi múlẹ̀, tí o sì dá mi láre;ìwọ ni o jókòó lórí ìtẹ́, o sì ṣe ìdájọ́ òdodo.

5. O bá àwọn orílẹ̀-èdè wí,o pa àwọn eniyan burúkú run,o sì pa orúkọ wọn rẹ́ títí lae.

6. O pa àwọn ọ̀tá run patapata, o sọ ìlú wọn di ahoro,o sì sọ wọ́n di ẹni ìgbàgbé.

7. Ṣugbọn OLUWA gúnwà títí lae,ó ti fi ìdí ìtẹ́ ìdájọ́ rẹ̀ múlẹ̀.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 9