Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 89:1-6 BIBELI MIMỌ (BM)

1. OLUWA, n óo máa kọrin ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ títí lae;n óo máa fi ẹnu mi kéde òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.

2. Nítorí pé, a ti fi ìdí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ múlẹ̀ títí lae;o sì ti fi ìdí òtítọ́ rẹ múlẹ̀ bí ojú ọ̀run.

3. O sọ pé, “Mo ti dá majẹmu kan pẹluẹni tí mo yàn,mo ti búra fún Dafidi, iranṣẹ mi, pé,

4. ‘N óo fi ìdí àwọn ọmọ rẹ múlẹ̀ títí lae,n óo sì gbé ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’ ”

5. Jẹ́ kí ojú ọ̀run máa kọrin ìyìn iṣẹ́ ìyanu rẹ, OLÚWA;kí àwọn eniyan mímọ́ sì máa kọrin ìyìn òtítọ́ rẹ.

6. Nítorí ta ni a lè fi wé ọ ní ọ̀run, OLUWA?Ta ni ó dàbí OLUWA láàrin àwọn ẹ̀dá ọ̀run?

Ka pipe ipin Orin Dafidi 89