Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 85:6-13 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Ṣé o ò ní tún sọ wá jí ni,kí àwọn eniyan rẹ lè máa yọ̀ ninu rẹ?

7. Fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ hàn wá, OLUWA;kí o sì fún wa ní ìgbàlà rẹ.

8. Jẹ́ kí n gbọ́ ohun tí Ọlọrun, OLUWA yóo wí,nítorí pé ọ̀rọ̀ alaafia ni yóo sọ fún àwọn eniyan rẹ̀,àní, àwọn olùfọkànsìn rẹ̀,ṣugbọn kí wọn má yipada sí ìwà òmùgọ̀.

9. Nítòótọ́, ìgbàlà rẹ̀ wà nítòsí fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀;kí ògo rẹ̀ lè wà ní ilẹ̀ wa.

10. Ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ati òtítọ́ yóo pàdé;òdodo ati alaafia yóo dì mọ́ ara wọn.

11. Òtítọ́ yóo rú jáde láti inú ilẹ̀;òdodo yóo sì bojú wolẹ̀ láti ojú ọ̀run.

12. Dájúdájú, OLUWA yóo fúnni ní ohun tí ó dára;ilẹ̀ wa yóo sì mú èso jáde lọpọlọpọ.

13. Òdodo yóo máa rìn lọ níwájú rẹ̀,yóo sì sọ ipasẹ̀ rẹ̀ di ọ̀nà.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 85