Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 78:31-48 BIBELI MIMỌ (BM)

31. Ọlọrun bínú sí wọn;ó pa àwọn tí ó lágbára jùlọ ninu wọn,ó sì lu àṣàyàn àwọn ọdọmọkunrin Israẹli pa.

32. Sibẹsibẹ wọ́n tún dẹ́ṣẹ̀;pẹlu gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, wọn kò gbàgbọ́.

33. Nítorí náà ó mú kí ọjọ́ ayé wọn pòórá bí afẹ́fẹ́;wọ́n sì lo ọjọ́ ayé wọn pẹlu ìjayà.

34. Nígbàkúùgbà tí ó bá ń pa wọ́n, wọn á wá a;wọn á ronupiwada, wọn á sì wá Ọlọrun tọkàntọkàn.

35. Wọn á ranti pé Ọlọrun ni àpáta ààbò wọn,ati pé Ọ̀gá Ògo ni olùràpadà wọn.

36. Ṣugbọn wọn kàn ń fi ẹnu wọn pọ́n ọn ni;irọ́ ni wọ́n sì ń pa fún un.

37. Ọkàn wọn kò dúró ṣinṣin lọ́dọ̀ rẹ̀;wọn kò sì pa majẹmu rẹ̀ mọ́.

38. Sibẹ, nítorí pé aláàánú ni, ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n,kò sì pa wọ́n run;ní ọ̀pọ̀ ìgbà ni ó dáwọ́ ibinu rẹ̀ dúró,tí kò sì fi gbogbo ara bínú sí wọn.

39. Ó ranti pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n,afẹ́fẹ́ lásán tí ń fẹ́ kọjá lọ, tí kò sì ní pada mọ́.

40. Ìgbà mélòó ni wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i ninu ijù,tí wọ́n sì bà á lọ́kàn jẹ́ ninu aṣálẹ̀!

41. Wọ́n dán an wò léraléra,wọ́n sì mú Ẹni Mímọ́ Israẹli bínú.

42. Wọn kò ranti agbára rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ranti ọjọ́ tí ó rà wọ́n pada lọ́wọ́ ọ̀tá;

43. nígbà tí ó ṣe iṣẹ́ abàmì ní ilẹ̀ Ijipti,tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní oko Soani.

44. Ó sọ omi odò wọn di ẹ̀jẹ̀,tí wọn kò fi lè mu omi wọn.

45. Ó rán ọ̀wọ́ eṣinṣin sí wọn tí ó jẹ wọ́n,ati ọ̀pọ̀lọ́ tí ó pa wọ́n run.

46. Ó mú kí kòkòrò jẹ èso ilẹ̀ wọn;eṣú sì jẹ ohun ọ̀gbìn wọn.

47. Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́;ó sì fi òjò dídì run igi Sikamore wọn.

48. Ó fi yìnyín pa mààlúù wọn;ó sì sán ààrá pa agbo aguntan wọn.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 78