Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 78:13-28 BIBELI MIMỌ (BM)

13. Ó pín òkun níyà, ó jẹ́ kí wọ́n kọjá láàrin rẹ̀;ó sì mú kí omi nàró bí òpó ńlá.

14. Ó fi ìkùukùu ṣe atọ́nà wọn ní ọ̀sán,ó fi ìmọ́lẹ̀ iná tọ́ wọn sọ́nà ní gbogbo òru.

15. Ó la àpáta ni aṣálẹ̀,ó sì fún wọn ní omi mu lọpọlọpọ bí ẹni pé láti inú ibú.

16. Ó mú ìṣàn omi jáde láti inú àpáta;ó sì mú kí ó ṣàn bí odò.

17. Sibẹsibẹ wọn ò dẹ́kun ẹ̀ṣẹ̀ dídá;wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá Ògo ninu aṣálẹ̀.

18. Wọ́n dán Ọlọrun wò ninu ọkàn wọn,wọ́n ń wá oúnjẹ tí yóo tẹ́ ìfẹ́ ọkàn wọn lọ́rùn.

19. Wọ́n sọ̀rọ̀ ìwọ̀sí sí Ọlọrun, wọ́n ní,“Ṣé Ọlọrun lè gbé oúnjẹ kalẹ̀ fún wa ninu aṣálẹ̀?

20. Lóòótọ́ ó lu òkúta tí omi fi tú jáde,tí odò sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣàn.Ṣé ó lè fún wa ní òkèlè pẹlu,àbí ó lè pèsè ẹran fún àwọn eniyan rẹ̀?”

21. Nítorí náà nígbà tí OLUWA gbọ́,inú bí i;iná mọ́ ìdílé Jakọbu,inú OLUWA sì ru sí àwọn ọmọ Israẹli;

22. nítorí pé wọn kò gba Ọlọrun gbọ́;wọn kò sì gbẹ́kẹ̀lé agbára ìgbàlà rẹ̀.

23. Sibẹ ó pàṣẹ fún ìkùukùu lókè,ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ọ̀run sílẹ̀.

24. Ó rọ òjò mana sílẹ̀fún wọn láti jẹ,ó sì fún wọn ní ọkà ọ̀run.

25. Ọmọ eniyan jẹ lára oúnjẹ àwọn angẹli;Ọlọrun fún wọn ní oúnjẹ àjẹtẹ́rùn.

26. Ó mú kí afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn fẹ́ ní ojú ọ̀run,ó sì fi agbára rẹ̀ darí afẹ́fẹ́ ìhà gúsù;

27. ó sì rọ̀jò ẹran sílẹ̀ fún wọn bí erùpẹ̀ ilẹ̀;àní, ẹyẹ abìyẹ́ bíi yanrìn etí òkun.

28. Ó mú kí wọn bọ́ sílẹ̀ láàrin ibùdó;yíká gbogbo àgọ́ wọn,

Ka pipe ipin Orin Dafidi 78