Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 71:4-20 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Ọlọrun mi, gbà mí lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú,àwọn alaiṣootọ ati ìkà.

5. Nítorí ìwọ OLUWA, ni ìrètí mi,OLUWA, Ọlọrun mi, ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé láti ìgbà èwe mi.

6. Ìwọ ni mo gbára lé láti inú oyún;ìwọ ni o mú mi jáde láti inú ìyá mi.Ìwọ ni n óo máa yìn nígbà gbogbo.

7. Mo di ẹni àmúpòwe fún ọpọlọpọ eniyan,ṣugbọn ìwọ ni ààbò mi tí ó lágbára.

8. Ẹnu mi kún fún ìyìn rẹ,ó kún fún ògo rẹ tọ̀sán-tòru.

9. Má ta mí nù ní ìgbà ogbó mi;má sì gbàgbé mi nígbà tí n kò bá lágbára mọ́.

10. Nítorí pé àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ mi,àwọn tí ń lépa ẹ̀mí mi ti pàmọ̀ pọ̀,

11. wọ́n ní, “Ọlọrun ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀;ẹ lé e, ẹ mú un;nítorí kò sí ẹni tí yóo gbà á sílẹ̀ mọ́.”

12. Ọlọrun, má jìnnà sí mi;yára, Ọlọrun mi, ràn mí lọ́wọ́!

13. Jẹ́ kí ojú ó ti àwọn alátakò mi, kí wọn parun;kí ẹ̀gàn ati ìtìjú bo àwọn tí ń wá ìpalára mi.

14. Ní tèmi, èmi ó máa ní ìrètí nígbà gbogbo,n óo sì túbọ̀ máa yìn ọ́.

15. N óo máa ṣírò iṣẹ́ rere rẹ,n óo máa ròyìn iṣẹ́ ìgbàlà rẹ tọ̀sán-tòru,nítorí wọ́n pọ̀ tóbẹ́ẹ̀ tí n kò lè mọ iye wọn.

16. N óo wá ninu agbára OLUWA Ọlọrun,n óo máa kéde iṣẹ́ òdodo rẹ, àní, iṣẹ́ òdodo tìrẹ nìkan.

17. Ọlọrun, láti ìgbà èwe mi ni o ti kọ́ mi,títí di òní ni mo sì ń polongo iṣẹ́ ìyanu rẹ,

18. Nisinsinyii tí mo ti dàgbà, tí ewú sì ti gba orí mi,Ọlọrun, má kọ̀ mí sílẹ̀,títí tí n óo fi ròyìn iṣẹ́ ńlá rẹ,àní, iṣẹ́ agbára rẹ, fún gbogbo àwọn ìran tí ń bọ̀.

19. Ọlọrun, iṣẹ́ òdodo rẹ kan ojú ọ̀run,ìwọ tí o ṣe nǹkan ńlá,Ọlọrun, ta ni ó dàbí rẹ?

20. O ti jẹ́ kí n rí ọpọlọpọ ìpọ́njú ńlá,ṣugbọn óo tún mú ìgbé ayé mi pada bọ̀ sípò;óo tún ti gbé mi dìde láti inú isà òkú.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 71