Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 68:13-26 BIBELI MIMỌ (BM)

13. ati àwọn tí ó wà ní ibùjẹ ẹran rí ìkógun pín:fadaka ni wọ́n yọ́ bo apá ère àdàbà;wúrà dídán sì ni wọ́n yọ́ bo ìyẹ́ rẹ̀.

14. Nígbà tí Olodumare tú àwọn ọba ká,ní òkè Salimoni, yìnyín bọ́.

15. Áà! Òkè Baṣani, òkè ńlá;Áà! Òkè Baṣani, òkè olórí pupọ.

16. Ẹ̀yin òkè olórí pupọ,kí ló dé tí ẹ̀ ń fi ìlara wo òkè tí Ọlọrun fẹ́ràn láti máa gbé,ibi tí OLUWA yóo máa gbé títí lae?

17. OLUWA sọ̀kalẹ̀ láti òkè Sinai sí ibi mímọ́ rẹ̀pẹlu ẹgbẹẹgbẹrun lọ́nà ẹgbẹrun kẹ̀kẹ́ ogun,ẹgbẹẹgbẹrun lọ́nà ẹgbẹrun.

18. Ó gun òkè gíga,ó kó àwọn eniyan nígbèkùn;ó gba ẹ̀bùn lọ́wọ́ àwọn eniyan,ati lọ́wọ́ àwọn ọlọ̀tẹ̀ pàápàá.OLUWA Ọlọrun yóo máa gbébẹ̀.

19. Ìyìn ni fún OLUWA, Ọlọrun ìgbàlà wa,tí ń bá wa gbé ẹrù wa lojoojumọ.

20. Ọlọrun tí ń gbani là ni Ọlọrun wa;OLUWA Ọlọrun ni ń yọni lọ́wọ́ ikú.

21. Dájúdájú, OLUWA yóo fọ́ orí àwọn ọ̀tá rẹ̀;yóo fọ́ àtàrí àwọn tí ń dẹ́ṣẹ̀.

22. OLUWA ní,“N óo kó wọn pada láti Baṣani,n óo kó wọn pada láti inú ibú omi òkun,

23. kí ẹ lè fi ẹsẹ̀ wọ́ àgbàrá ẹ̀jẹ̀ àwọn ọ̀tá yín,kí àwọn ajá yín lè lá ẹ̀jẹ̀ wọn bí ó ti wù wọ́n.”

24. A ti rí ọ, Ọlọrun, bí o tí ń yan lọ,pẹlu ọ̀wọ́ èrò tí ń tẹ̀lé ọ lẹ́yìn.Ẹ wo Ọlọrun mi, ọba mi,bí ó ti ń yan wọ ibi mímọ́ rẹ̀,

25. àwọn akọrin níwájú,àwọn onílù lẹ́yìn,àwọn ọmọbinrin tí ń lu samba láàrin.

26. “Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọrun ninu àwùjọ eniyan,ẹ̀yin ìran Israẹli, ẹ fi ọpẹ́ fún OLUWA.”

Ka pipe ipin Orin Dafidi 68