Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 66:9-17 BIBELI MIMỌ (BM)

9. ẹni tí ó dá wa sí tí a fi wà láàyè,tí kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa yẹ̀.

10. Nítorí ìwọ, Ọlọrun, ti dán wa wò;o ti dán wa wò bíi fadaka tí a dà ninu iná.

11. O jẹ́ kí á bọ́ sinu àwọ̀n;o sì di ẹrù wúwo lé wa lórí.

12. O jẹ́ kí àwọn eniyan máa gùn wá lórí mọ́lẹ̀,a ti la iná ati omi kọjá;sibẹsibẹ o mú wa wá sí ibi tí ilẹ̀ ti tẹ́jú.

13. N óo wá sinu ilé rẹ pẹlu ọrẹ ẹbọ sísun;n óo sì san ẹ̀jẹ́ mi fún ọ.

14. Ẹ̀jẹ́ tí mo jẹ́,tí mo sì fi ẹnu mi sọ nígbà tí mo wà ninu ìpọ́njú.

15. N óo fi ẹran àbọ́pa rú ẹbọ sísun sí ọ,èéfín ẹbọ àgbò yóo rú sókè ọ̀run,n óo fi akọ mààlúù ati òbúkọ rúbọ.

16. Ẹ wá gbọ́, gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọrun,n óo sì ròyìn ohun tí ó ṣe fún mi.

17. Mo ké pè é,mo sì kọrin yìn ín.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 66