Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Dafidi 66:4-18 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Gbogbo ayé ní ń sìn ọ́;wọ́n ń kọ orin ìyìn fún ọ,wọ́n ń kọ orin ìyìn sí orúkọ rẹ.”

5. Ẹ wá wo ohun tí Ọlọrun ṣe,iṣẹ́ tí ó ń ṣe láàrin ọmọ eniyan bani lẹ́rù.

6. Ó sọ òkun di ìyàngbẹ ilẹ̀,àwọn eniyan fi ẹsẹ̀ rìn kọjá láàrin odò.Inú wa dùn níbẹ̀ nítorí ohun tí ó ṣe.

7. Nípa agbára rẹ̀ ó ń jọba títí lae.Ó ń ṣọ́ àwọn orílẹ̀-èdè lójú mejeeji,kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má gbéraga sí i.

8. Ẹ yin Ọlọrun wa, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè,ẹ jẹ́ kí á gbọ́ ìró ìyìn rẹ̀;

9. ẹni tí ó dá wa sí tí a fi wà láàyè,tí kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa yẹ̀.

10. Nítorí ìwọ, Ọlọrun, ti dán wa wò;o ti dán wa wò bíi fadaka tí a dà ninu iná.

11. O jẹ́ kí á bọ́ sinu àwọ̀n;o sì di ẹrù wúwo lé wa lórí.

12. O jẹ́ kí àwọn eniyan máa gùn wá lórí mọ́lẹ̀,a ti la iná ati omi kọjá;sibẹsibẹ o mú wa wá sí ibi tí ilẹ̀ ti tẹ́jú.

13. N óo wá sinu ilé rẹ pẹlu ọrẹ ẹbọ sísun;n óo sì san ẹ̀jẹ́ mi fún ọ.

14. Ẹ̀jẹ́ tí mo jẹ́,tí mo sì fi ẹnu mi sọ nígbà tí mo wà ninu ìpọ́njú.

15. N óo fi ẹran àbọ́pa rú ẹbọ sísun sí ọ,èéfín ẹbọ àgbò yóo rú sókè ọ̀run,n óo fi akọ mààlúù ati òbúkọ rúbọ.

16. Ẹ wá gbọ́, gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọrun,n óo sì ròyìn ohun tí ó ṣe fún mi.

17. Mo ké pè é,mo sì kọrin yìn ín.

18. Bí mo bá gba ẹ̀ṣẹ̀ láyè ní ọkàn mi,OLUWA ìbá tí gbọ́ tèmi.

Ka pipe ipin Orin Dafidi 66